Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 49:29-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọnyóò di gbígbà; ilé wọn yóò diìsínípò padà pẹ̀lú ẹrù àti ràkúnmí wọn.Àwọn ọkùnrin yóò ké pè wọ́n;‘Ìparun ní ibi gbogbo.’

30. “Sálọ kíákíá, dúró nínú ihòìwọ tí ò ń gbé Ásórì,”báyìí ni Olúwa wí.“Nebukadinésárì Ọba Bábílónì ti dojú ìjà kọ ọ́.

31. “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀ èdèkan pẹ̀lú ìrọ̀rùn, èyítí ó dúró pẹ̀lú ìgboyà;”báyìí ní Olúwa wí.“Orílẹ̀ èdè tí kò ní yálà gbàgede tàbí irin,àwọn ènìyàn re ń dágbé.

32. Àwọn ràkunmí á di ẹrùàti àwọn agbo àgùntàn, wọ́n á di ìkógun.Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́.Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,”báyìí ní Olúwa wí.

33. “Ásọ́rì yóò di ibi ìdọdẹ àwọnakáta, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé,kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”

34. Èyí ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run èyí tí ó tọ Jeremáyà wòlíì wá nípa Élámù ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekáyà Ọba Júdà:

35. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run alágbára sọ:“Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Élámù,ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.

Ka pipe ipin Jeremáyà 49