Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 49:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Ísọ̀ sí ìhòòhòèmi kò ní bo ibi ìkọ̀kọ rẹnítorí kí o máa baà fi ara rẹ pamọ́.Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àtiàwọn ará ilé rẹ yóò parun.Wọn kò sì ní sí mọ́.

11. Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀èmi yóò dábòbo ẹ̀mí wọn.Àwọn opó rẹ gan an lè gbékẹ̀lẹ́ mi.”

12. Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ife náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mu un.

13. Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bósírà yóò bayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ẹgún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”

14. Èmi ti gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa:A rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀ èdè láti sọ.Ẹ kó ara yín jọ láti dojúkọ ọ́, ẹ dìde fún ogun.

Ka pipe ipin Jeremáyà 49