Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 48:10-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. “Ìfibú ni fún ẹni tí ó dúró láti ṣe iṣẹ́ Olúwa,ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀sílẹ̀.

11. “Móábù ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wábí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀,tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejìkò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí.Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ,òórùn rẹ̀ kò yí padà.

12. Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,”ni Olúwa wí,“nígbà tí n ó rán àwọn tí ó da ọtí láti inú àwọn ìgòtí wọ́n ó sì dà á síta;Wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo,wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.

13. Nígbà náà Móábù yóò sì tú u nítorí kémósì,bí ojú ti í ti ilé Ísírẹ́lìnígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Bétélì.

14. “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘ajagun ni wá,alágbára ní ogun jíjà’?

15. A ó pa Móábù run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀;a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,”ni Ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

16. “Ìṣubú Móábù súnmọ́;ìpọ́njú yóò dé kánkán.

17. Ẹ dárò fún, gbógbó ẹ̀yin tí ó yí i kágbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó.Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹtítóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’

18. “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ,kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ,ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Díbónì,nítorí tí ẹni tí ó pa Móábù runyóò dojúkọ ọ́yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.

19. Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran,ìwọ tí ń gbé ní Áróà.Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà‘kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’

20. Ojú ti Móábù nítorí tí a wó o lulẹ̀,ẹ hu, sì kígbe síta!Ámónì kéde péa pa Móábù run.

21. Ìdájọ́ ti dé sí Pílátéùsórí Hólónì, Jáhásà àti Mẹ́fátì,

22. sórí Díbónì, Nébò àti Bẹti Díbílátaímù

23. sórí Kíríátaímù, Bẹti Gámù àti Bẹti Méónì,

24. sórí Kéríótì àti Bóásì,sórí gbogbo ìlú Móábù, nítòsí àti ní ọ̀nà jínjìn.

25. A gé ìwo Móábù kúrò,apá rẹ̀ dá,”ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 48