Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 46:5-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Kí ni nǹkan tí mo tún rí?Wọ́n bẹ̀rù,wọ́n sì ń padà sẹ́yìn,wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun.Wọ́n sá,wọn kò sì bojú wẹ̀yìn,ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,”ni Olúwa wí.

6. “Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ,tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà.Ní Gúṣù ní ibi odò Ẹ́fúrétàwọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.

7. “Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Náílì,tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n ọn nì?

8. Éjíbítì dìde bí odò náà,bí omi odò tí ń ru.Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’Èmi yóò pa orílẹ̀ èdè àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.

9. Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin,ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́.Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú,ẹ̀yin ọkùnrin Kúṣì àti Pútì tí ń gbé ọ̀kọ̀;àti ẹ̀yin ọkùnrin Lìdíà tí ń fa ọrun.

10. Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun,ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀.Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn,títí yóò fi pa òrùngbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun yóò rúbọní ilẹ̀ Gúṣù ní odò Ẹ́fúrétà.

11. “Gòkè lọ sí Gílíádì, kí o sì mú ìkunra,ìwọ wúndíá Éjíbítì.Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn,kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.

12. Àwọn orílẹ̀ èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ,igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé.Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ,àwọn méjèèjì yóò sì dìjọ ṣubú papọ̀.”

13. Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremáyà wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadinésárì Ọba Bábílónì láti lọ dojú ìjà kọ Éjíbítì:

14. “Kéde èyí ní Éjíbítì, sì sọ ọ́ ní Nígídò,sọ ọ́ ní Mémífísì àti Táfánésì:‘Dúró sí àyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀,nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’

15. Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú?Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.

16. Wọn yóò máa ṣubú léralérawọn yóò máa ṣubú lu ara wọn.Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padàsí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa,kúrò níbi idà àwọn aninilára.’

Ka pipe ipin Jeremáyà 46