Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 44:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Obìnrin náà fi kun-un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rúbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”

20. Wàyí o, Jeremáyà sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,

21. “Ṣe Ọlọ́run kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Júdà àti àwọn ìgboro Jérúsálẹ́mù láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn bàbá rẹ, àwọn Ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.

22. Nígbà tí Ọlọ́run kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìbínú gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 44