Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 44:12-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Júdà, tí wọ́n ṣetán láti lọ Éjíbítì. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.

13. Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Éjíbítì pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-àrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jérúsálẹ́mù.

14. Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Júdà tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Éjíbítì tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Júdà, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mèlòó kan.”

15. Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Éjíbítì, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremáyà.

16. “Wọn sì wí pé: Àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ni orúkọ Olúwa.

17. Dájúdájú; à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe: A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run; à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn Ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Júdà àti ni àwọn ìgboro Jérúsálẹ́mù. Nígbà naà àwa ní ounjẹ púpọ̀ a sì ṣe rere a kò sì rí ibi

18. Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí ayaba ọrun sílẹ̀ àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”

19. Obìnrin náà fi kun-un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rúbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”

20. Wàyí o, Jeremáyà sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,

Ka pipe ipin Jeremáyà 44