Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 4:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Tí ó bá jẹ́ lóòtọ́ àti òdodo niìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láàyè,nígbà náà ni orílẹ̀ èdè yóò di alábùkún fúnnípaṣẹ̀ rẹ àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.

3. Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Júdà àti Jérúsálẹ́mù.“Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí,kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.”

4. Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwakọ ọkàn rẹ ní ilàẹ̀yin ènìyàn Júdà àti gbogbo ènìyàn Jérúsálẹ́mù,bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná,nítorí ibi tí o ti ṣekì yóò sí ẹni tí yóò pa á.

5. “Kéde ní Júdà, kí o sì polongo ní Jérúsálẹ́mù, kí o sì wí pé:‘fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀. Kí o sì kígbe,‘kó ara jọ pọ̀!Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’

Ka pipe ipin Jeremáyà 4