Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 36:29-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Kí o sì wí fún Jéhóíákímù Ọba Júdà pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èése tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lòótọ́ ni Ọba Bábílónì yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”

30. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí níti Jéhóíákímù Ọba Júdà pé: Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dáfídì, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.

31. Èmi ó sì jẹ òun àti irú ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ níyà nítorí àìṣedédé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jérúsálẹ́mù àti àwọn ènìyàn Júdà, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’ ”

32. Nígbà náà ni Jeremáyà mú ìwé kíká mìíràn fún Bárúkì akọ̀wé ọmọ Neráyà, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremáyà gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jéhóíákímù Ọba Júdà ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.

Ka pipe ipin Jeremáyà 36