Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 32:42-44 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

42. “Nítorí bayìí ni Olúwa wí: Gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa ti wọn wá sórí wọn.

43. Lẹ́ẹ̀kan síi, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Bábílónì.’

44. Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí i pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Bẹ́ńjámínì àti ní ìlú kékèké tí ó yí Jérúsálẹ́mù ká àti ní ìlú Júdà àti ní ìlú ọwọ́ òkè orílẹ̀ èdè ní ìhà gúṣù olókè ilẹ̀ àti ní Gúsù, nítorí èmi ó mú ìgbékùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 32