1. Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremáyà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2. “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3. Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì àti Júdà kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4. Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Ísírẹ́lì àti Júdà:
5. “Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“ ‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrìláìṣe igbe àlàáfíà.
6. Béèrè kí o sì rí:Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí?Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrintí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí,tí ojú gbogbo wọn sì fàro fún ìrora?