Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 3:9-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nítorí ìwà èérí Ísírẹ́lì kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.

10. Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Júdà arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olótìtọ́,” ni Olúwa wí.

11. Olúwa wí fún mi pé, “Ísírẹ́lì aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Júdà tí ó ní Ìgbàgbọ́ lọ.

12. Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá:“ ‘Yípadà, Ísírẹ́lì aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí.‘Ojú mi kì yóò le sí yín mọ́,nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí.

13. Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ,o ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ,o ti wá ojú rere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjìlábẹ́ gbogbo igikígi,tí ó tẹ́wọ́, o kò sì gbọ́ràn sí mi lẹ́nu,’ ”ni Olúwa wí.

14. “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Síónì.

15. Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́ àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.

16. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa’ kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.

17. Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jérúsálẹ́mù ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀ èdè yóò péjọ sí Jérúsálẹ́mù láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle burúkú wọn mọ́.

18. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Júdà yóò darapọ̀ mọ́ ilé Ísírẹ́lì. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.

19. “Èmi fúnra mi sọ wí pé,“ ‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrinkí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.

Ka pipe ipin Jeremáyà 3