Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 29:13-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.

14. Èmi yóò sì mú yín kúrò ní ìgbékùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀ èdè àti ibi gbogbo tí mo ti lé yín jáde. Èmi yóò sì kó yín padà sí Jérúsálẹ́mù ibi tí mo ti kó jáde lọ sí ilé àtìpó.”

15. Ẹ lè sọ pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Bábílónì.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 29