Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 25:33-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò sọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.

34. Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkúnẹ̀yin olùsọ́ àgùntàn, ẹ yí nínú eruku,ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran,nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé,ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.

35. Àwọn olùsọ́ àgùntàn kì yóò ríbi sálọkì yóò sì sí àsálà fún olórí agbo ẹran.

36. Gbọ́ igbe àwọn olùsọ́ àgùntàn,àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olóríagbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.

37. Pápá oko tútù yóò di asánnítorí ìbínú ńlá Olúwa.

38. Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀,ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn anínilára,àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.

Ka pipe ipin Jeremáyà 25