8. “ ‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èṣo ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Ṣedekáyà Ọba Júdà, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jérúsálẹ́mù, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Éjíbítì.
9. Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi sí gbogbo ìjọba ayé, ẹni ẹ̀sín àti ẹni ẹ̀tẹ́, ẹni àbùkù àti ẹni èpè ní ibi gbogbo tí Èmi bá lé wọn sí.
10. Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-àrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’ ”