Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 22:16-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ó gbéjà òtòsì àti aláìní,ohun gbogbo sì dára fún un.Ìyẹn ha kọ́ ni mímọ́ mi túmọ̀ sí?”ni Olúwa wí.

17. “Ṣùgbọ́n ojú àti ọkàn rẹwà lára rẹ̀ ní èrè àìsòtítọ́láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”

18. Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehóíákímù ọmọ Jòsáyà, Ọba Júdà:“Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’Wọn kì yóò sọ̀fọ̀ fún un:wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe kábíyèsí!’

19. A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́tí a wọ́ sọnù gba ti ẹnubodèJérúsálẹ́mù.”

20. “Gòkè lọ sí Lẹ́bánónì, kígbe sítakí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Básánì,kí o kígbe sókè láti Ábárímù,nítorí a ti run gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ túútúú.

21. Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu,ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ,ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.

22. Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ,gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbékùn,nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.

23. Ìwọ tí ń gbé ‘Lẹ́bánónì,’tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kédárì,ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ,ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!

Ka pipe ipin Jeremáyà 22