Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 21:5-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.

6. Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-àrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.

7. Olúwa sọ pé lẹ́yìn ìyẹn, èmi yóò fi Sedekáyà Ọba Júdà, àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó yọ nínú ìṣẹ̀lẹ̀ ogun àti ìyàn lé Ọba Nebukadinésárì àti Bábílónì àti gbogbo ọ̀ta wọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òun yóò sì fi idà pa wọ́n, kì yóò sì ṣàánú wọn.’

8. “Síwájú síi, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.

9. Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-àrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Bábílónì tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.

10. Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí níyà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún Ọba Bábílónì, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’

11. “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé Ọba Júdà pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.

12. Ilé Dáfídì èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ:“ ‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀;yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í láraẹni tí a ti jà lólèbí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná.Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jóláìsí ẹni tí yóò pa á.

13. Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jérúsálẹ́mùìwọ tí o gbé lórí àfonífojìlórí olókúta tí ó tẹ́jú,Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojú kọ wá?”

14. Èmi yóò jẹ ẹ́ níyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ni Olúwa wí.Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀;ìyẹn yóò jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’ ”

Ka pipe ipin Jeremáyà 21