Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 17:5-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Báyìí ni Olúwa wí:“Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn,tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran ara,àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa

6. Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá,kò ní rí ire, nígbà tí ó bá dé yóòmáa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ ihà,ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.

7. “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrinnáà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.

8. Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadòtí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odòkò sí ìbẹ̀rù fún-un nígbà ooru,gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutùkò sí ìjáyà fún-un ní ọdún ọ̀dábẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”

9. Ọkàn kún fún ẹ̀tàn ju ohungbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lèwòsàn, tani èyí lè yé?

Ka pipe ipin Jeremáyà 17