Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 17:3-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹpẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ópọ̀ káàkiri orílẹ̀ èdè yín.

4. Láti ipaṣẹ̀ àìṣedéédé yín ni ẹ̀yinyóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù.Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yínbí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀; nítoríẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”

5. Báyìí ni Olúwa wí:“Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn,tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran ara,àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa

6. Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá,kò ní rí ire, nígbà tí ó bá dé yóòmáa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ ihà,ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.

7. “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrinnáà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.

8. Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadòtí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odòkò sí ìbẹ̀rù fún-un nígbà ooru,gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutùkò sí ìjáyà fún-un ní ọdún ọ̀dábẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”

9. Ọkàn kún fún ẹ̀tàn ju ohungbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lèwòsàn, tani èyí lè yé?

10. “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èròinú ọmọ ènìyàn láti ṣan èrèiṣẹ́ rẹ̀ fún-un, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”

11. Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé niọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ niọ̀nà àìsòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti níòpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.

12. Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ní ibi ilé mímọ́ wa.

13. Olúwa olùgbẹ́kẹ̀lé Ísírẹ́lìgbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ niojú ó tì: gbogbo àwọn tí ó padàṣẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ọ́ kọorúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́nti kọ Olúwa orísun omi ìyè wọn sílẹ̀.

14. Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò diẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóòdi ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.

15. Wọ́n sọ fún mi wí pé:“Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà?Jẹ́ kí ó di ìmúsẹ báyìí.”Ni Olúwa wí.

16. Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùsọàgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmikò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tíó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.

17. Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ niààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú

Ka pipe ipin Jeremáyà 17