Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 13:7-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nígbà náà ni mo lọ sí Pérátì mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsín yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.

8. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:

9. “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Júdà àti ìgbéraga ńlá ti Jérúsálẹ́mù.

10. Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.

Ka pipe ipin Jeremáyà 13