Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 13:4-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fi wé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Pérátì kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.

5. Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Pérátì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.

6. Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi: Lọ sí Pérátì kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.

7. Nígbà náà ni mo lọ sí Pérátì mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsín yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.

8. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:

9. “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Júdà àti ìgbéraga ńlá ti Jérúsálẹ́mù.

10. Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.

11. Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Ísírẹ́lì àti gbogbo ilé Júdà mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’

Ka pipe ipin Jeremáyà 13