Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 10:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omilọ́run a sì pariwo, ó mú kí ìkuùkù rusókè láti òpin ayé: ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14. Gbogbo ènìyàn jẹ́ aláìlóye àti aláìnímọ̀,ojú sì ti gbogbo alágbára pẹ̀lú ère rẹ̀,èrú ni ère rẹ̀, kò sì sí ẹ̀mí nínú wọn.

15. Asán ni wọ́n, iṣẹ́ yẹ̀yẹ́ sì ni;nígbà tí ìdájọ́ wọn bá dé, wọn yóò ṣègbé.

16. Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jákọ́bù kò sìdàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dáohun gbogbo àti Ísírẹ́lì tí ó jẹ́ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọogun ni orúkọ rẹ̀.

17. Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ìwọ tí o ń gbé ní abẹ́ ààbò.

18. Nítorí èyí ni Olúwa wí:“Ní àkókò yìí,èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbéilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njúbá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”

19. Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi!Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ nimọ sọ fún ara mi,“Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”

20. Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já.Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́Kò sí ẹnìkankan pẹ̀lú mi mọ́, báyìí kò sí ẹni tí yóòná àgọ́ mi tàbí ṣe ibùgbé fún mi

Ka pipe ipin Jeremáyà 10