Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 1:7-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Olúwa sọ fún mi pé, má ṣe sọ pé ọmọdé lásán ni mí. O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ.

8. Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9. Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsìnyìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ

10. Wòó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀ èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti má a kọ́, àti láti máa gbìn.

11. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé“Kí ni o rí Jeremáyà?” Mo sì dáhùn wí pé “Mo rí ẹ̀ka igi álímọ́ńdi”

12. Olúwa sì wí fún mi pé, “ó ti rí i bí ó se yẹ, torí pé mo ti ń sọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúsẹ.”

13. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ́kèjì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.

14. Olúwa, sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti da ìdààmú sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.

15. Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀ èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí.Àwọn Ọba wọn yóò wágbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú-ọ̀nà à bá wọléJérúsálẹ́mù. Wọn ó sì dìde sí gbogboàyíká wọn àti sí gbogbo àwọnìlú Júdà.

16. Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lóríàwọn ènìyàn mi nítorí ìwàbúburú wọn nípa kíkọ̀ mísílẹ̀, nípa rírúbọ sí Ọlọ́runmìíràn àti sínsin àwọn ohuntí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.

17. “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pa lásẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọn dẹ́rù bà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.

18. Ní òní èmi ti sọ ọ́ di orílẹ̀ èdè alágbára, òpó ìrin àti odi idẹ sí àwọn Ọba Júdà, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.

Ka pipe ipin Jeremáyà 1