Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 50:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ṣùgbọ́n Jósẹ́fù wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?

20. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbérò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbérò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.

21. Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèṣè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.

22. Jósẹ́fù sì ń gbé ní Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láàyè fún àádọ́fà (110) ọdún.

23. Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Éfúrémù-Àwọn ọmọ Mákírì, ọmọkùnrin Mánásè ni a sì gbé le eékún Jósẹ́fù nígbà tí ó bí wọn.

24. Nígbà náà ni Jóṣẹ́fù wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹrẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú-un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Ábúráhámù, Ísáákì àti Jákọ́bù.”

25. Jóṣẹ́fù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì búra májẹ̀mu kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”

26. Báyìí ni Jóṣẹ́fù kú nígbà tí ó pé àádọ́fà (110) ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n se òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Éjíbítì.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 50