Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 18:30-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ábúráhámù sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n (30) ni rí níbẹ̀ ńkọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, Èmi kì yóò pa ìlú run.”

31. Ábúráhámù wí pé, “Níwọ̀n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀ṣíwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ńkọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”

32. Ábúráhámù sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni bá tí ó jẹ́ olódodo ńkọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, Èmi kì yóò pa á run.”

33. Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tan, Ábúráhámù sì padà sílé.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 18