Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 9:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn mo dójú bolẹ̀, mo kígbe pé, “Áà! Olúwa Ọlọ́run! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Ísírẹ́lì pẹ̀lú dída ìbínú gbígbónà rẹ sórí Jérúsálẹ́mù?”

9. Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Ísírẹ́lì àti Júdà pọ gan an ni; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀sílẹ̀ àti àìsòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’

10. Nítorí náà, n kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú n kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n N ó dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”

11. Ọkùnrin aláṣọ funfun pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ́ rẹ̀ sì wá jábọ̀ pé, “Mo ti ṣe ohun tí o pa láṣẹ.”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 9