Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 48:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn: Ní òpin àríwá, Dánì yóò ni ìpín kan; èyí yóò tẹ̀lé ọ̀nà Hétílónù sí létí Hámátì; Hásárì Énánù àti ààlà àríwá tí Dámásíkù tí ó kángun sí Hámátì yóò jẹ́ ara ààlà rẹ̀ láti ìhà ìlà oòrùn títí lọ sí ìhà ìwọ̀ oòrùn.

2. “Àsárì yóò ní ìpín kan; yóò jẹ́ ààlà agbégbé dánì láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ oòrùn.

3. “Náfítalì yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Ásárì láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ̀ oòrùn.

4. “Mánásè yóò ní ìpín; èyí yóò jẹ́ ààlà ti agbégbé Náfátalì láti ìlà oòrùn sí ìwọ̀ oòrùn.

5. “Éfúráímù yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Mánásè láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ oòrùn.

6. “Rúbẹ́nì yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Éfúráímù láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 48