Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 41:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ìta ibi mímọ́ ni férémù onígun mẹ́rin pẹ̀lú ìkan tí ó wà ní ibi mímọ́ jùlọ rí bákan náà.

22. Pẹpẹ ìrúbọ kan tí a fi igi ṣe wà, gíga rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì, àwọn igun rẹ̀, ìsàlẹ̀ rẹ̀ àti ògiri rẹ́ jẹ́ igi. Ọkùnrin náà sọ fún mi pé, “Èyí yìí ní tẹ́ḿpìlì tí ó wà ní iwájú Olúwa.”

23. Ìta ibi mímọ́ àti ibi mímọ́ jùlọ ni ilẹ̀kùn méjì papọ̀.

24. Lẹ̀kùn kọ̀ọ̀kan ní ewé méjìméjì, ewé méjì tí a gbe kọ́ fún ẹnu ọ̀nà kọ̀ọ̀kan.

25. Ní ẹnu ilẹ̀kùn ní ìta ibi mímọ́ ni àwọn kérúbù àti igi ọ̀pẹ tí a fín bí ti àwọn tí a fín si àwọn ara ògiri, ìbòrí tí á fí igi ṣe wà ní iwájú ẹnu ọ̀nà ilé ní ìta.

26. Ní ẹ̀gbẹ́ àwọn ògiri ẹnu ọ̀nà ní àwọn fèrèsé tóóró pẹ̀lú igi ọ̀pẹ tí a fín ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì wà. Àwọn yàrá ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ ilé Ọlọ́run náà ni ìbòrí tí a fi igi ṣe.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 41