Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 28:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tírè pé, ‘Báyìí ní Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè simiìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run;Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣàní àárin gbùngbùn òkun.”Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà,bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.

3. Ìwọ gbọ́n ju Dáníẹ́lì lọ bí?Ṣé kò sí àsírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?

4. Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹàti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákànínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.

5. Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀,ọkàn rẹ gbé sókèNitorí ọrọ̀ rẹ.

6. “ ‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n,pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run

7. Èmi yóò mú kí àwọn àjòjì dìde sí ọ,ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀ èdè;wọn yóò yọ idà wọn sí ọẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹwọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 28