Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 27:31-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹwọn yóò wọ aṣọ yíyawọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lúìkoro ọkàn nítorí rẹpẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.

32. Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùn réré ẹkún fún ọwọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé:“Ta ni ó dàbí Tírèèyí tí ó parun ní àárin òkun?”

33. Nígbà tí ọjà títà rẹ ti òkun jáde wáìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè lọ́rùnìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹsọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.

34. Ní ìsinsìn yìí tí òkun fọ ọ túútúúnínú ibú omi;nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹní àárin rẹ,ni yóò ṣubú.

35. Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbéní erékùṣù náà sí ọàwọn ọba wọn yóò sì dìjì,ìyọnu yóò sì yọ ní ojú wọn.

36. Àwọn oníṣòwò láàrin àwọn orílẹ̀ èdè dún bí ejò sí ọìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rùìwọ kì yóò sì sí mọ́ láéláé.’ ”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 27