Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 27:24-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Wọ̀nyí ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oniṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ oníyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi kédárì ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.

25. “ ‘Àwọn ọkọ̀ Táṣíṣì ní èròní ọjà rẹa ti mú ọ gbilẹ̀a sì ti ṣe ọ́ lógoní àárin gbungbun òkun

26. Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọwá sínú omi ńlá.Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ní àárin gbùngbùn òkun.

27. Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ,àwọn atọ́kọ̀ rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ.Àwọn oníbárà rẹ àti gbogbo àwọnjagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹàti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹtí ó wà ní àárin rẹyóò rì sínú àárin gbùngbùn òkunní ọjọ́ ìparun rẹ.

28. Ilẹ̀ etí òkun yóò mìnítorí ìró igbe àwọn atọ́kọ̀ rẹ.

29. Gbogbo àwọn alájẹ̀àwọn atukọ̀àti àwọn atọ́kọ̀ ojú òkun;yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn,wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.

30. Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọwọn yóò sì sunkún kíkorò lé ọ lóríwọn yóò ku eruku lé orí ara wọnwọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.

31. Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹwọn yóò wọ aṣọ yíyawọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lúìkoro ọkàn nítorí rẹpẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.

32. Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùn réré ẹkún fún ọwọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé:“Ta ni ó dàbí Tírèèyí tí ó parun ní àárin òkun?”

33. Nígbà tí ọjà títà rẹ ti òkun jáde wáìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè lọ́rùnìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹsọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.

34. Ní ìsinsìn yìí tí òkun fọ ọ túútúúnínú ibú omi;nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹní àárin rẹ,ni yóò ṣubú.

35. Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbéní erékùṣù náà sí ọàwọn ọba wọn yóò sì dìjì,ìyọnu yóò sì yọ ní ojú wọn.

36. Àwọn oníṣòwò láàrin àwọn orílẹ̀ èdè dún bí ejò sí ọìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rùìwọ kì yóò sì sí mọ́ láéláé.’ ”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 27