Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 25:10-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Èmi yóò fi Móábù pẹ̀lú àwọn ará Ámónì lé àwọn ènìyàn ìlà oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ámónì láàrin orílẹ̀ èdè gbogbo;

11. Èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣsẹ sí Móábù lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”

12. “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí pé: ‘Nítorí pé Édómù gbẹ̀san lára ilé Júdà, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa síse bẹ́ ẹ̀,

13. nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Édómù èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi sófo láti Temanì dé Dédánì yóò ti ipa idà ṣsubú.

14. Èmi yóò gbẹ̀san lára Édómù láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Ísírẹ́lì, wọn sì se ṣsi Édómù gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi: wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Ọlọ́run wí.’ ”

15. “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Fílísítíà hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìjà gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Júdà run,

16. nítorí náà báyìí ní Olúwa Ọlọ́run wí pé: Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Fílísítíà Èmi yóò sì ké àwọn ará Kérétì kúrò, Èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.

17. Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.’ ”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 25