Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 23:30-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. ni ó mú èyí wá sórí rẹ, nítorí tí ìwọ ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si orílẹ̀ èdè, o sì fi àwọn òrìṣà rẹ́ ara rẹ jẹ.

31. Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn; Èmi yóò sì fi aago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.

32. “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè:“Ìwọ yóò mu nínú aago ẹ̀gbọ́n rẹ,aago tí ó tóbi tí ó sì jinnú:yóò mú ìfisẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá,nítorí tí aago náà gba nǹkan púpọ̀.

33. Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́,aago ìparun àti ìsọdahoroaago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaríà.

34. Ìwọ yóò mú un, ni àmugbẹ;ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya.Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.

35. “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ̀n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí iwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ́ àti aṣẹ́wó rẹ.”

36. Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Óhólà àti Óhólíbà? Nítorí náà dojú kọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 23