Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 21:10-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. a ti pọ́n fún pípa,a sì dan an kí ó lè máa kọ bí mọ̀nàmọ́ná!“ ‘Àwa yóò ha si ọ̀pá aládé ọmọ mi Júdà? Idà kẹ́gàn gbogbo ọ̀pá.

11. “ ‘Idà ní a yàn láti pọ́n,kí ó lè ṣe é gbá mú;a pọ́n ọn a sì dan án,ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.

12. Sunkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn,nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi;yóò wá sórí gbogbo ọmọ aládé Ísírẹ́lììbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn minítorí idà náà;nítorí náà lu oókan àyà rẹ.

13. “ ‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Júdà èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ ṣíwájú mọ́ ńkọ́? Ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’

14. “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn,sọ tẹ́lẹ̀ kí ó sì fí ọwọ́ lu ọwọ́Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì,kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta.Ó jẹ́ idà fún ìpànìyànidà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọpọ̀Tí yóò sé wọn mọ́ níhìnín àti lọ́hùnnún.

15. Kí ọkàn kí ó lè yọ́kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀,mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparunÁà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná,a gbá a mú fún ìparun.

16. Ìwọ idà, jà sí ọ̀túnkí o sì jà sí òsìlọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 21