Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 19:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ aládé Ísírẹ́lì

2. wí pé:“ ‘Èwo nínú abo kìnnìnu ni ìyá rẹ̀ ní àárin àwọn kìnnìún yóòkù?Ó sùn ní àárin àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.

3. Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára,ó kọ́ ọ láti sọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.

4. Àwọn orílẹ̀ èdè gbọ́ nípa rẹ̀,wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú ààfin wọn.Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Éjíbítì.

5. “ ‘Nígbà tí abo kìnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì já sí asán,ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.

6. Ó sì ń rìn káàkiri láàrin àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára,o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.

7. Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọ̀n ìlú wọn di ahoro.Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.

8. Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀ èdè tó yìí ká dìde sí i,wọn ta ẹ̀wọ̀n fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 19