Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 18:11-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. (bó tilẹ̀ jẹ́ pé baba rẹ kò se irú rẹ̀):“Ó ń jẹun lojúbọ lórí òkè gíga,o ba ìyàwó aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.

12. Ó ni àwọn talákà àti aláìní lára,ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí,o gbójú sókè sí òrìṣà,ó sì ń ṣe ohun ìríra.

13. Ó ń fowó ya ni pẹ̀lú èlé ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù.Ǹjẹ́ irú ọkunrin yìí wa le è yè bí? Kò lè wá láàyè! Nítorí pé ó ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.

14. “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe bẹ́ẹ̀:

15. “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gígatàbí kò gbójú sókè sí àwọnòrìṣà ilé Ísírẹ́lì, tí kò sì báiyàwó aládùúgbò rẹ̀ jẹ́

16. tí kò ni ẹnikẹ́ni lára,tí kò hùwà ibití kò gba èlé tàbí kò fipá jalèṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ,tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.

17. Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀,kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù,ó ń pa òfin mi mọ́,ó sì ń tẹ̀lé àwọn àsẹ mi.Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 18