Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 17:22-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. “ ‘Báyìí ní Olúwa Ọlọ́run wí: Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lori igi Kédàrí gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó sẹ̀sẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.

23. Ní ibi gíga òkè Ísírẹ́lì ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso yóò wa di igi Kédárì tí ó lọ́lá. Orírsìírísìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀

24. Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkurú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé.“ ‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì se e.’ ”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 17