Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 8:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ọlọ́run rẹ̀. Fi ìpè sí ẹnu rẹ!Ẹyẹ igún wà lórí ilé Olúwanítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú,wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.

2. Ísírẹ́lì kígbe pè mí‘Áà! Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́!’

3. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀

4. Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ miwọ́n yan ọmọ aládé láì si ìmọ̀ mi nibẹ̀.Wọ́n fi fàdákà àti wúràṣe ère fún ara wọn,kì a ba le ké wọn kúrò.

5. Ọmọ-mààlu rẹ ti ta ọ́ nù ìwọ Ṣamáríà! Ju ère tí o gbẹ́ nùÌbínú mi ń ru sí wọn:yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?

6. Ísírẹ́lì ni wọ́n ti wá!Ère yìí—agbẹ́gilére ló ṣe éÀní ère Samáríà, ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́.

7. “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́wọ́n sì ká ìjìIgi ọkà kò lórí,kò sì ní mú oúnjẹ wá.Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkààwọn àlejò ni yóò jẹ.

8. A ti gbé Ísírẹ́lì mì,Báyìí, ó sì ti wà láàrin àwọn orílẹ̀ èdèbí ohun èlò tí kò wúlò.

9. Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Síríàgẹ́gẹ́ bí ẹhànnà kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń rìn kiri.Éfúráímù ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.

10. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárin orílẹ̀ èdèÈmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsìn yìíWọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànùlọ́wọ́ ìnílára ọba alágbára.

Ka pipe ipin Hósíà 8