Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 2:19-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé.Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àtiòtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.

20. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní ìsòtítọ́ìwọ yóò sì mọ Olúwa

21. “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà”ni Olúwa wí.“Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùnàwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;

22. Ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà,wáìnì tuntun àti òróró lóhùnGbogbo wọn ó sì dá Jésírẹ́lì lóhùn.

23. Èmi ó sì gbìn-ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náàÈmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘àànú Gbà.’Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’ ”

Ka pipe ipin Hósíà 2