Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hágáì 2:19-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pómégíránátè, àti igi ólífì kò ì tíì so èso kankan.“ ‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún-un yin.’ ”

20. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hágáì wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé:

21. “Sọ fún Sérúbábélì baálẹ̀ Júdà pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.

22. Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run; Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́sin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”

23. Olúwa àwọn wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn ọmọ-ogun iwọ ìránṣẹ́ mi Sérúbábélì ọmọ Séítíélì, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

Ka pipe ipin Hágáì 2