Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hábákúkù 3:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ní ìrúnú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.

13. Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,àti láti gba ẹni àmì òróró rẹ là;Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,fifi ìpìlẹ̀ hàn títí dé ọrùn

14. pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹnígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀jáde láti tú wá ká:ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ talákà run ní kọ̀kọ̀.

15. Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn òkun já,O tẹ òkun mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀,ìwọ fi àwọn ẹsin rẹ̀ rin òkun já,ó sì mu omi ńlá jáde okiki omi ńlá

16. Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì,ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà;ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ,ẹ̀sẹ̀ mi sì wárìrì,mo dúró ni ìdákẹ́jẹ́ fún ọjọ́ ìdààmúláti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.

Ka pipe ipin Hábákúkù 3