Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sírà 7:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ẹ́sírà yìí gòkè wá láti Bábílónì. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfìn Mósè, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.

7. Ní ọdún keje ọba Aritaṣéṣéṣì díẹ̀ lára àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Léfì, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹ́ḿpìlì náà gòkè wá sí Jérúsálẹ́mù.

8. Ní oṣù kánùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Ẹ́sírà dé sí Jérúsálẹ́mù.

9. Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Bábílónì ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jérúsálẹ́mù ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.

Ka pipe ipin Ẹ́sírà 7