Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sírà 5:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ṣùgbọ́n ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba Ṣáírúsì ọba Bábílónì, ọba Ṣáírúsì pàṣẹ pé kí a tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́.

14. Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni tí ó lọ bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran-ọ̀sìn pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn-án lọ́wọ́ fún tẹ́ḿpìlì Ọlọ́run ní Jérúsálẹ́mù. Kí wọn sì mú wá sí tẹ́ḿpílì ní BábílónìNígbà náà ọba Sáírúsì kó wọn fún ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣesibásárì, ẹni tí ó ti yàn gẹ́gẹ́ bí i Baálẹ̀,

15. ó sì sọ fún un pé, “Kó àwọn ohun èlò yìí kí o lọ, kí o sì kó wọn sí inú ilé Olúwa ní Jérúsálẹ́mù, pẹ̀lú kí ẹ sì tún ilé Ọlọ́run kọ́ sí ipò o rẹ̀.”

16. Nígbà náà ni Ṣesibásásárì náà wá, ó sí fi ìpìlẹ̀ ilé Ọlọ́run tí ó wá ní Jérúsálẹ́mù lẹ́lẹ̀, láti ìgbà náà àní títí di ìsínsìn yìí ni o ti n bẹ ní kíkọ́ ṣùgbọ́n, kò sí tí ì parí tán.

17. Nísinsìn yìí tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí ní ilé ìṣúra ọba ní Bábílónì láti rí bí ọba Ṣáírúsì fi àṣẹ lélẹ̀ lóòótọ́ láti tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́ ní Jérúsálẹ́mù. Nígbà náà jẹ́ kí ọba kó fi ìpinnu rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí ránṣẹ́ sí wa.

Ka pipe ipin Ẹ́sírà 5