Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sírà 5:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà wòlíì Hágáì àti wòlíì Ṣekaráyà, láti ìrán Ìdó, sọ àṣọtẹ́lẹ̀ sí àwọn ará Júù ní Júdà àti Jérúsálẹ́mù ní orúkọ Ọlọ́run Ísírẹ́lì tí ẹ̀mí rẹ̀ ń bẹ lára wọn.

2. Nígbà náà Ṣerubábélì ọmọ Ṣéálítíélì àti Jéṣúà ọmọ Jóṣádákì gbáradì fún iṣẹ́ àti tún ilé Ọlọ́run ní Jérúsálẹ́mù kọ́. Àwọn wòlíì Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, tí wọ́n ń ràn wọ́n lọ́wọ́.

3. Ní àkókò náà Táténáì, Baálẹ̀ ti agbègbè Yúfúrátè àti Ṣétarì-Bóṣénáì àti àwọn ẹgbẹ́gbẹ́ wọn lọ sí ọ̀dọ̀ wọn Wọ́n sì béèrè pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún tẹ́ḿpìlì yìí kọ́ àti láti tún odi yìí mọ?”

4. Wọ́n sì tún béèrè pé, “Kí ni orúkọ àwọn ọkùnrin tí ó ń kọ́ ilé yìí?”

Ka pipe ipin Ẹ́sírà 5