Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 3:43-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

43. “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;ìwọ ń parun láì sí àánú.

44. Ìwọ ti fi ìkuukù bo ara rẹpé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.

45. Ó ti sọ wá di èérí àti ààtànláàrin orílẹ̀ èdè gbogbo.

46. “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọngbòòrò sí wa.

47. Àwa ti jìyà àti ìparun,nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”

48. Omijé ń ṣàn ní ojú mi bí odònítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49. Ojú mi kò dá fún omijé,láì sinmi,

50. títí ìgbà tí Olúwa síjú wolẹ̀láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.

51. Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn minítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52. Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìídẹ mí bí ẹyẹ.

53. Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihòwọ́n sì ju òkúta lù mí.

54. Orí mi kún fún omi,mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 3