39. Kí ló dé tí ẹ̀dá alàyè ṣe ń kùnnígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
40. Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa kí a sì dán an wò,kí a sì tọ Olúwa lọ.
41. Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókèsí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:
42. Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jìn wá.
43. “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;ìwọ ń parun láì sí àánú.
44. Ìwọ ti fi ìkuukù bo ara rẹpé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45. Ó ti sọ wá di èérí àti ààtànláàrin orílẹ̀ èdè gbogbo.
46. “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọngbòòrò sí wa.
47. Àwa ti jìyà àti ìparun,nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”