Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 3:37-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀tí Olúwa kò bá fàṣẹ sí i.

38. Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu ẹni ńláni dídára àti búburú tí ń wá?

39. Kí ló dé tí ẹ̀dá alàyè ṣe ń kùnnígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

40. Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa kí a sì dán an wò,kí a sì tọ Olúwa lọ.

41. Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókèsí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:

42. Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jìn wá.

43. “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;ìwọ ń parun láì sí àánú.

44. Ìwọ ti fi ìkuukù bo ara rẹpé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.

45. Ó ti sọ wá di èérí àti ààtànláàrin orílẹ̀ èdè gbogbo.

46. “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọngbòòrò sí wa.

47. Àwa ti jìyà àti ìparun,nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”

48. Omijé ń ṣàn ní ojú mi bí odònítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49. Ojú mi kò dá fún omijé,láì sinmi,

50. títí ìgbà tí Olúwa síjú wolẹ̀láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 3