Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 3:15-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkoròàti ìdààmú bí omi.

16. Ó ti fi òkúta kán ẹyín mi;ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.

17. Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;Mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.

18. Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọàti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19. Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,ìkorò àti ìbànújẹ́.

20. Mo ṣèrántí wọn,ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.

21. Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkànàti nítorí náà ní mo nírètí.

22. Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,nítorí àánú rẹ kì í kùnà.

23. Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;títóbi ni òdodo rẹ̀.

24. Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́

25. Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,sí àwọn tí ó ń wá a.

26. Ó dára kí a ní ṣùúrùfún ìgbàlà Olúwa.

27. Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgànígbà tí ó wà ní èwe.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 3