Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 3:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njúpẹ̀lú ọ̀pá ìbínú.

2. Ó ti lémi jáde ó sì mú mi rìnnínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;

3. Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí misíwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

4. Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran ara mi gbóó sì tún ṣẹ́ egungun mi.

5. Ó ti fi mí sí ìgbèkùn ó sì ti yí mi kápẹ̀lú ìkorò àti làálàá.

6. Ó mú mi gbé nínú òkùnkùnbí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

7. Ó ti tì mí mọ́lé nítorí náà n kò le è sálọ;ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀

8. Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,ó kọ àdúrà mi.

9. Ó fi búlọ́kù òkúta dí ọ̀nà mi;ó sì mú ọ̀nà mi wọ́

10. Bí i béárì tí ó dùbúlẹ̀,bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.

11. Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ó fi mi sílẹ̀ láì sí ìrànlọ́wọ́.

12. Ó fa ọfà rẹ̀ yọó sì fi mí sohun ìtafàsí.

13. Ó fa ọkàn mí yapẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 3