Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 1:10-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ légbogbo ìní rẹ;o rí àwọn ìlú abọ̀rìṣàtí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—àwọn tí o ti kọ̀ sílẹ̀láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11. Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérorabí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;wọ́n fi ohun ìní wọn se pàsípààrọ̀ oúńjẹláti mú wọn wà láàyè.“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12. “Kò ha jẹ́ nǹkankan sí i yín?Gbogbo ẹ̀yin tí ń ré kọjá,Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyàtí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún miní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

13. “Ó rán iná láti òkèsọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,ó sì yí mi padà.Ó ti pa mí láramó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.

14. “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di síṣopọ̀ sí àjàgà;ọwọ́ ọ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù.Ó sì ti fi mí léàwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.

15. “Olúwa kọàwọn akọni mi sílẹ̀,ó rán àwọn ológun lòdì sí mikí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Júdà.

16. “Ìdí nìyí tí mo fi ń sunkúntí omijé sì ń dà lójú mi,Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sími,kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.Àwọn ọmọ mi di aláìnínítorí ọ̀ta ti borí.”

17. Ṣíónì na ọwọ́ jáde,ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jákọ́bùpé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀ta fún unJérúsálẹ́mù ti diohun aláìmọ́ láàrin wọn.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 1