Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 40:31-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Mósè, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ lò ó láti fi wẹ ọwọ́ àti ẹṣẹ̀ wọn.

32. Wọ́n máa ń wẹ̀ nígbàkugbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ tàbí tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

33. Mósè sì gbé àgbàlá tí ó yí Àgọ́ náà kà ró àti pẹpẹ, ó sì ta aṣọ títa ti ẹnu ọ̀nà sí àgbàlá náà. Bẹ́ẹ̀ Mósè ṣe parí iṣẹ náà

34. Nígbà náà ni àwọ̀ọsánmọ̀ bo àgọ́ àjọ, ògo Olúwa bo Àgọ́ náà.

35. Mósè kò sì lè wọ inú Àgọ́ àjọ, nítorí àwọ́ọ́sánmọ̀ wà lórí rẹ, ògo Olúwa sì ti kún inú Àgọ́ náà.

36. Ní gbogbo ìrìnàjò àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nígbàkugbà tí a ba ti fa ikuuku àwọ̀ọsánmọ̀ náà sókè kúrò lórí Àgọ́, wọ́n máa ń jáde lọ;

37. ṣùgbọ́n tí àwọ̀ọsánmọ̀ kò bá gòkè wọn kò ní jáde títí di ọjọ́ tí ó bá gòkè.

38. Nítorí náà àwọ̀ọsánmọ̀ Olúwa wà lórí Àgọ́ ní ọ̀sán, iná sì wà nínú àwọ̀ọsánmọ̀ ní òru, ní ojú gbogbo ilé Ísírẹ́lì ní gbogbo ìrìnàjò wọn.

Ka pipe ipin Ékísódù 40